'Àwa òṣèré àná ti ṣiṣẹ́ tán, fìkan-makan ló kù tí wọ́n n ṣe lóde òní'

Àkọlé fídíò,
'Àwa òṣèré àná ti ṣiṣẹ́ tán, fìkan-makan ló kù tí wọ́n n ṣe lóde òní'

Agba osẹre, Mamoudou Akanbi Ehysse, ti ọpọ tun mọ si Mr Okeke, ti sọ fun BBC pe ọna to pọ ni Ọlọrun ti fi itan kikọ kẹ oun – ninu bọọlu gbigba, ere itage, ati gẹgẹ bi oloye ni aafin ọba.

Ọgbẹni Okeke sọ pe awọn osẹre nigba atijọ, to fi mọ awọn akọrin, lo ti ṣe ere tan.

O ni amulumala lo ku lode oni, nitori pe pupọ ninu awọn ere ati orin ti wọn n gbe jade lo n ṣi awọn ọmọde lọna.

“Nigba atijọ, awọn iṣẹlẹ inu ile kaluku la fi n ṣe ere.”

Yatọ si ere ori itage ṣiṣe, ọMr Okeke tun gba bọọlu fun ilẹ Dahomey, to ti di orilẹ-ede Benin Republic bayii, laarin 1960 si 1970.

O ni owo ni awọn agbabọọlu ode oni n gbá, kii sẹ bọọlu.